Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 152

Ilé Tó Máa Mú Ìyìn Wá Bá Ọ

Ilé Tó Máa Mú Ìyìn Wá Bá Ọ

(1 Àwọn Ọba 8:27; 1 Kíróníkà 29:14)

  1. 1. Jèhófà, ìwọ lo dá ọ̀run,

    Síbẹ̀, ọ̀run kò lè gbà ọ́.

    Ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ ilé yìí,

    Jọ̀ọ́, jẹ́ kẹ́mìí rẹ wà níbí.

    Àwa tí a jẹ́ ènìyàn rẹ

    Ti kọ́ ibi ìjọsìn yìí.

    Ìjọsìn rẹ ń mú inú wa dùn;

    Jọ̀ọ́, tẹ́wọ́ gba ìjọsìn wa.

    (ÀSOPỌ̀)

    Ìwọ náà lo fún wa

    Ní gbogbo ohun tá a ní.

    Inú ohun tó o fún wa

    La ti ń fún ọ, Bàbá.

    (ÈGBÈ)

    A dúpẹ́ fún gbogbo ‘hun tó o ṣe,

    Jèhófà, à ń kọrin yìn ọ́.

    O ti jẹ́ ká lè kọ́ ilé yìí

    Tó máa mú ìyìn wá bá ọ.

  2. 2. O mọ̀ pé a fẹ́ kọ́ ilé kan

    Tó máa mú ìyìn wá bá ọ,

    Tó máa ṣèrànwọ́ fẹ́gbẹ́ ará,

    Táá sì ran àwọn míì lọ́wọ́.

    A ti kọ́ ilé náà tán báyìí.

    Iṣẹ́ ṣì pọ̀ gan-an láti ṣe.

    Ràn wá lọ́wọ́ ká lè ṣiṣẹ́ tí

    Ọmọ rẹ gbé lé wa lọ́wọ́.

    (ÀSOPỌ̀)

    A fi àkókò wa

    Àti ohun ìní wa

    Bọlá fún ọ torí pé

    Ìwọ nìkan ló yẹ.

    (ÈGBÈ)

    A dúpẹ́ fún gbogbo ‘hun tó o ṣe,

    Jèhófà, à ń kọrin yìn ọ́.

    O ti jẹ́ ká lè kọ́ ilé yìí

    Tó máa mú ìyìn wá bá ọ.