Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 33

Ohun Tí Ìjọba Ọlọ́run Máa Ṣe fún Aráyé

Ohun Tí Ìjọba Ọlọ́run Máa Ṣe fún Aráyé

Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso. Láìpẹ́, ó máa tún ayé yìí ṣe. Jẹ́ ká wo díẹ̀ lára àwọn ohun rere tá a máa gbádùn nínú Ìjọba Ọlọ́run.

1. Báwo ni Ìjọba Ọlọ́run ṣe máa mú kí àlàáfíà àti ìdájọ́ òdodo jọba láyé?

Nígbà ogun Amágẹ́dọ́nì, Jésù tó jẹ́ Ọba Ìjọba Ọlọ́run máa pa àwọn èèyàn burúkú run, ó sì máa fòpin sí gbogbo ìjọba èèyàn. (Ìfihàn 16:14, 16) Tó bá dìgbà yẹn, ohun tó wà ní Sáàmù 37:10 máa ṣẹ láìkù síbì kan. Ó ní: “Láìpẹ́, àwọn ẹni burúkú ò ní sí mọ́.” Jésù máa lo Ìjọba Ọlọ́run láti mú kí àlàáfíà àti ìdájọ́ òdodo jọba ní gbogbo ayé.​—Ka Àìsáyà 11:4.

2. Báwo ni ayé ṣe máa rí nígbà tí gbogbo èèyàn bá ń ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́?

Lábẹ́ Ìjọba Ọlọ́run, “àwọn olódodo ni yóò jogún ayé, wọn yóò sì máa gbé inú rẹ̀ títí láé.” (Sáàmù 37:29) Fojú inú wo bí ayé ṣe máa rí nígbà tí gbogbo èèyàn bá jẹ́ olódodo, tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tí wọ́n sì nífẹ̀ẹ́ ara wọn! Àwọn èèyàn ò ní máa ṣàìsàn mọ́, wọ́n á sì wà láàyè títí láé.

3. Kí ni Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe lẹ́yìn tí àwọn èèyàn burúkú bá ti pa run?

Lẹ́yìn tí àwọn èèyàn burúkú bá ti pa run, Jésù máa ṣàkóso ayé fún ẹgbẹ̀rún (1,000) ọdún. Nígbà yẹn, Jésù àtàwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) tí wọ́n máa bá a ṣàkóso á sọ gbogbo èèyàn tó wà láyé di pípé. Tí ẹgbẹ̀rún ọdún yẹn bá fi máa parí, ayé á ti di Párádísè, àwọn èèyàn tó jẹ́ aláyọ̀ torí pé wọ́n ń gbọ́ràn sí Jèhófà lẹ́nu ló sì máa wà ní gbogbo ayé. Lẹ́yìn náà, Jésù máa dá àkóso pa dà fún Jèhófà Bàbá rẹ̀. ‘Orúkọ Jèhófà á wá di mímọ́’ lọ́nà tó ga jù lọ. (Mátíù 6:9, 10) Ó máa wá hàn kedere pé Alákòóso tó dáa ni Jèhófà, ó sì nífẹ̀ẹ́ àwa èèyàn. Jèhófà á wá pa Sátánì àtàwọn ẹ̀mí èṣù run, títí kan gbogbo àwọn èèyàn tó ń ta ko Ìjọba Ọlọ́run. (Ìfihàn 20:7-10) Tí Ìjọba Ọlọ́run bá ti tún ayé yìí ṣe, kò tún ní sí ìṣòro kankan mọ́ títí láé!

KẸ́KỌ̀Ọ́ JINLẸ̀

Jẹ́ ká wo ohun tó mú kó dá wa lójú pé Ọlọ́run máa lo Ìjọba rẹ̀ láti ṣe gbogbo àwọn ohun rere tí Bíbélì sọ pé ó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú.

4. Ìjọba Ọlọ́run máa fòpin sí ìjọba èèyàn

“Èèyàn ti jọba lórí èèyàn sí ìpalára rẹ̀.” (Oníwàásù 8:9) Jèhófà máa lo Ìjọba rẹ̀ láti fòpin sí ìyà tí ìjọba èèyàn fi ń jẹ aráyé.

Ka Dáníẹ́lì 2:44 àti 2 Tẹsalóníkà 1:6-8, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • Kí ni Jèhófà àti Jésù Ọmọ rẹ̀ máa ṣe sí ìjọba èèyàn àtàwọn tó ń ti ìjọba èèyàn lẹ́yìn?

  • Báwo ni ohun tó o mọ̀ nípa Jèhófà àti Jésù ṣe mú kó dá ẹ lójú pé wọ́n máa ṣe ohun tó tọ́ àtohun tó yẹ fún gbogbo èèyàn?

5. Jésù ni Ọba tó yẹ wá

Jésù ni Ọba Ìjọba Ọlọ́run, ó sì máa ṣe ọ̀pọ̀ nǹkan tó máa ṣe aráyé láǹfààní. Wo FÍDÍÒ yìí kó o lè rí bí Jésù ṣe fi hàn pé ó ń wu òun gan-an láti ran àwa èèyàn lọ́wọ́ àti pé ó máa lo agbára tí Ọlọ́run fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀.

Nígbà tí Jésù wà láyé, ó jẹ́ ká mọ àwọn nǹkan tí Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe. Èwo lára àwọn ohun rere tó wà nísàlẹ̀ yìí ló ń wù ẹ́ jù? Ka àwọn ẹsẹ Bíbélì tó wà níwájú ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn ohun rere náà.

NÍGBÀ TÍ JÉSÙ WÀ LÁYÉ, Ó . . .

LÁTỌ̀RUN, JÉSÙ MÁA . . .

  • mú kí ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ oúnjẹ wà láyé, ó sì máa kárí gbogbo èèyàn.​—Sáàmù 72:16.

  • jí àwọn òkú dìde, àwọn èèyàn ò sì ní máa kú mọ́.​—Ìfihàn 21:3, 4.

6. Ìjọba Ọlọ́run máa mú káyé tura gan-an

Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe àwọn nǹkan tí Ọlọ́run ní lọ́kàn láti ṣe fún àwa èèyàn níbẹ̀rẹ̀. Àwọn èèyàn á máa gbé ayé títí láé. Wo FÍDÍÒ yìí kó o lè rí bí Jèhófà ṣe máa lo Ọmọ rẹ̀, Jésù, láti ṣe àwọn ohun tó ní lọ́kàn fún àwa èèyàn.

Ka Sáàmù 145:16, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

  • Báwo ló ṣe rí lára ẹ bó o ṣe mọ̀ pé Jèhófà máa “fún gbogbo ohun alààyè ní ohun tí wọ́n ń fẹ́”?

ÀWỌN KAN SỌ PÉ: “Táwa èèyàn bá fọwọ́ sowọ́ pọ̀, a lè yanjú àwọn ìṣòro tó wà láyé fúnra wa.”

  • Àwọn ìṣòro wo ni Ìjọba Ọlọ́run máa yanjú, àmọ́ tó jẹ́ pé ìjọba èèyàn ò lè yanjú wọn láé?

KÓKÓ PÀTÀKÌ

Ọlọ́run máa lo Ìjọba rẹ̀ láti ṣe àwọn ohun tó ní lọ́kàn níbẹ̀rẹ̀ fún àwa èèyàn. Ó máa sọ gbogbo ayé di Párádísè, àwọn èèyàn rere nìkan ló máa wà ní gbogbo ayé, wọ́n á sì máa jọ́sìn Jèhófà títí láé.

Kí lo rí kọ́?

  • Báwo ni Ìjọba Ọlọ́run ṣe máa sọ orúkọ Jèhófà di mímọ́?

  • Kí ló mú kó dá wa lójú pé Ọlọ́run máa lo Ìjọba rẹ̀ láti ṣe gbogbo àwọn ohun rere tí Bíbélì sọ pé ó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú?

  • Èwo lára àwọn ohun rere tí Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe ló ń wù ẹ́ jù?

Ohun tó yẹ kó o ṣe

ṢÈWÁDÌÍ

Ka ìwé yìí kó o lè mọ ohun tí Amágẹ́dọ́nì jẹ́.

“Kí Ni Ogun Amágẹ́dọ́nì?” (Àpilẹ̀kọ orí ìkànnì)

Ka ìwé yìí kó o lè mọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ nígbà ẹgbẹ̀rún ọdún ìṣàkóso Jésù àti ní òpin ẹgbẹ̀rún ọdún náà.

“Kí Ni Yóò Ṣẹlẹ̀ ní Ọjọ́ Ìdájọ́?” (Ilé Ìṣọ́, September 1, 2012)

Wo fídíò yìí kó o lè rí bí àwọn ìdílé ṣe lè máa ronú nípa àwọn ohun rere tí Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe.

Wo Ara Rẹ Bíi Pé O Wà ní Párádísè (1:50)

Ka ìtàn tí àkòrí ẹ̀ sọ pé, “Ọ̀pọ̀ Ìbéèrè Ń Jà Gùdù Lọ́kàn Mi,” kó o lè rí bí ọkùnrin kan tó máa ń bá ìjọba fa wàhálà ṣe rí ìdáhùn àwọn ìbéèrè tó ń wá.

“Bíbélì Máa Ń Yí Ìgbésí Ayé Àwọn Èèyàn Pa Dà” (Ilé Ìṣọ́, January 1, 2012)